22. Ọlọ́run mi rán ańgẹ́lì i rẹ̀, ó sì dí àwọn kìnnìún lẹ́nu. Wọn kò le è pamí lára, nítorí a rí mi gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀ ní iwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò hu ìwà ìbàjẹ́ kan níwájú rẹ ìwọ ọba.”
23. Inú ọba dùn gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a mú Dáníẹ́lì jáde wá láti inú ihò. Nígbà tí a mú Dáníẹ́lì jáde nínú ihò, kò sí ojú ọgbẹ́ kan ní ara rẹ̀, nítorí tí ó gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run rẹ̀.
24. Ọba pàṣẹ pé, kí a mú àwọn alátakò Dáníẹ́lì wá, kí a jù wọ́n sí inú ihò kìnnìún, pẹ̀lú ìyàwó àti àwọn ọmọ wọn. Kí wọn tó dé ìsàlẹ̀ ihò, kìnnìún lágbára lórí i wọn, wọ́n sì fọ́ gbogbo egungun wọn.
25. Nígbà náà, ni Dáríúsì ọba kọ̀wé sí gbogbo ènìyàn, orílẹ̀ èdè àti gbogbo jákèjádò ilẹ̀ náà:“Kí ire yín máa pọ̀ sí i!
26. “Mo gbé àsẹ kan jáde wí pé: ní gbogbo agbègbè ìjọba mi, gbogbo ènìyàn gbọdọ̀ bẹ̀rù, kí wọn kí ó sì bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Dáníẹ́lì.“Nítorí òun ni Ọlọ́run alààyèÓ sì wà títí ayé;Ìjọba rẹ̀ kò le è parunìjọba rẹ̀ kò ní ìpẹ̀kun
27. Ó ń yọ ni, ó sì ń gba ni là;ó ń ṣe iṣẹ́ àmì àti ìyanuní ọ̀run àti ní ayé.Òun ló gba Dáníẹ́lì làkúrò lọ́wọ́ agbára kìnnìún.”
28. Dáníẹ́lì sì ṣe rere ní àkókò ìjọba Dáríúsì àti àkókò ìjọba Sáírúsì ti Páṣíà.