Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 6:18-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nígbà náà ni ọba padà sí ààfin rẹ̀, ó sì lo gbogbo òru náà láì jẹun, kò sì gbọ orin kankan, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le è ṣùn ní òru ọjọ́ náà.

19. Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, ni ọba dìde ó sì sáré lọ sí ibi ihò kìnnìún náà.

20. Nígbà tí ó sún mọ́ ibi ihò náà ní ibi tí Dáníẹ́lì wà, ó pe Dáníẹ́lì pẹ̀lú ìtara pé, “Dáníẹ́lì, ìránṣẹ́ Ọlọ́run alààyè, ṣé Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn tọ̀sán tòru, lè gbà ọ́ lọ́wọ́ ọ kìnnìún bí?”

21. Dáníẹ́lì sì dáhùn wí pé, “Ọba kí ẹ pẹ́!

22. Ọlọ́run mi rán ańgẹ́lì i rẹ̀, ó sì dí àwọn kìnnìún lẹ́nu. Wọn kò le è pamí lára, nítorí a rí mi gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀ ní iwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò hu ìwà ìbàjẹ́ kan níwájú rẹ ìwọ ọba.”

23. Inú ọba dùn gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a mú Dáníẹ́lì jáde wá láti inú ihò. Nígbà tí a mú Dáníẹ́lì jáde nínú ihò, kò sí ojú ọgbẹ́ kan ní ara rẹ̀, nítorí tí ó gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run rẹ̀.

24. Ọba pàṣẹ pé, kí a mú àwọn alátakò Dáníẹ́lì wá, kí a jù wọ́n sí inú ihò kìnnìún, pẹ̀lú ìyàwó àti àwọn ọmọ wọn. Kí wọn tó dé ìsàlẹ̀ ihò, kìnnìún lágbára lórí i wọn, wọ́n sì fọ́ gbogbo egungun wọn.

25. Nígbà náà, ni Dáríúsì ọba kọ̀wé sí gbogbo ènìyàn, orílẹ̀ èdè àti gbogbo jákèjádò ilẹ̀ náà:“Kí ire yín máa pọ̀ sí i!

26. “Mo gbé àsẹ kan jáde wí pé: ní gbogbo agbègbè ìjọba mi, gbogbo ènìyàn gbọdọ̀ bẹ̀rù, kí wọn kí ó sì bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Dáníẹ́lì.“Nítorí òun ni Ọlọ́run alààyèÓ sì wà títí ayé;Ìjọba rẹ̀ kò le è parunìjọba rẹ̀ kò ní ìpẹ̀kun

27. Ó ń yọ ni, ó sì ń gba ni là;ó ń ṣe iṣẹ́ àmì àti ìyanuní ọ̀run àti ní ayé.Òun ló gba Dáníẹ́lì làkúrò lọ́wọ́ agbára kìnnìún.”

28. Dáníẹ́lì sì ṣe rere ní àkókò ìjọba Dáríúsì àti àkókò ìjọba Sáírúsì ti Páṣíà.

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 6