Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 6:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó dára lójú Dáríúsì láti yan ọgọ́fà àwọn baálẹ̀ sórí ìjọba,

2. pẹ̀lú alákòóso mẹ́ta, Dáníẹ́lì sì jẹ́ ọ̀kan nínú un wọn, kí àwọn baálẹ̀ lè wá máa jẹ́ ààbọ̀ fún wọn, kí ọba má ba à ní ìpalára.

3. Dáníẹ́lì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ láàrin àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ nítorí ẹ̀mí tí ó tayọ wà lára rẹ̀ dé bi pé ọba sì ń gbérò láti fi ṣe olórí i gbogbo ìjọba.

4. Nítorí èyí, gbogbo àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ ń gbérò láti wá ẹ̀ṣẹ̀ kà sí Dáníẹ́lì lọ́rùn nínú ètò ìṣèjọba rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan kà sí i lọ́rùn, wọn kò rí ìwà ìbàjẹ́ kankan tí ó ṣe, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ kò sì ní ìwà ìjáfara.

5. Nígbẹ̀yìn ni àwọn ọkùnrin wọ̀nyí sọ wí pé, “Àwa kò ní rí ìdí kankan láti kà ẹ̀ṣẹ̀ sí i lọ́rùn, àfi èyí tí ó bá ní í ṣe pẹ̀lú òfin Ọlọ́run rẹ̀.”

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 6