25. “Èyí ni àkọlé náà tí a kọ:MENE, MENE, TÉKÉLÌ, PÉRÉSÍNÌ
26. “Èyí ni nǹkan tí ọ̀rọ̀ náà túmọ̀ sí: Mene: Ọlọ́run ti sírò ọjọ́ ìjọba rẹ. Ó sì ti mú u wá sí òpin.
27. Tékélì: A ti gbé ọ lórí òṣùwọ̀n, ìwọ kò sì tó ìwọ̀n.
28. Pérésínì: A ti pín ìjọba rẹ a sì ti fi fún àwọn Médíà àti àwọn Páṣíà.”
29. Nígbà náà ni Beliṣáṣárì pàṣẹ pé kí a wọ Dáníẹ́lì ní aṣọ eléṣèé àlùkò, kí a sì fi ẹ̀gbà wúrà sí i lọ́rùn, a sì kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí kẹta ní ìjọba rẹ̀.
30. Ní alẹ́ ọjọ́ náà ni a pa Beliṣáṣárì, ọba Bábílónì.
31. Dáríúsì ará Médíánì sì gba ìjọba nígbà tí ó di ọmọ ọdún méjìlélọ́gọ́ta (62).