Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 5:25-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. “Èyí ni àkọlé náà tí a kọ:MENE, MENE, TÉKÉLÌ, PÉRÉSÍNÌ

26. “Èyí ni nǹkan tí ọ̀rọ̀ náà túmọ̀ sí: Mene: Ọlọ́run ti sírò ọjọ́ ìjọba rẹ. Ó sì ti mú u wá sí òpin.

27. Tékélì: A ti gbé ọ lórí òṣùwọ̀n, ìwọ kò sì tó ìwọ̀n.

28. Pérésínì: A ti pín ìjọba rẹ a sì ti fi fún àwọn Médíà àti àwọn Páṣíà.”

29. Nígbà náà ni Beliṣáṣárì pàṣẹ pé kí a wọ Dáníẹ́lì ní aṣọ eléṣèé àlùkò, kí a sì fi ẹ̀gbà wúrà sí i lọ́rùn, a sì kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí kẹta ní ìjọba rẹ̀.

30. Ní alẹ́ ọjọ́ náà ni a pa Beliṣáṣárì, ọba Bábílónì.

31. Dáríúsì ará Médíánì sì gba ìjọba nígbà tí ó di ọmọ ọdún méjìlélọ́gọ́ta (62).

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 5