Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 65:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,”ni Olúwa wí.“Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńláwọ́n sì ṣe mí lẹ́gbin ní òkè kékeré,Èmi yóò wọ́n ọ́n sí wọn nítanẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”

8. Ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí òjé sì tún wà nínú àpólà gírépùtí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘má ṣe bà á jẹ́,ohun dáradára sì kù sínú rẹ̀,’bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi;Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.

9. Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jákọ́bù,àti láti Júdà àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n ọn nì;àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn,ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.

10. Ṣárónì yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran,àti àfonífojì Ákò yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran,fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.

11. “Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀tí ẹ sì gbàgbé òkè mímọ́ mi,tí ó tẹ́ tábìlì fún ọrọ̀tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,

Ka pipe ipin Àìsáyà 65