Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 47:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ṣọ̀kalẹ̀, jókòó nínú eruku,wúndíá ọmọbìnrin Bábílónì;jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀ láìsí ìtẹ́,ọmọbìnrin àwọn ará Bábílónì.A kì yóò pè ọ́ ní aláìlókun àti ẹlẹgẹ́ mọ́.

2. Mú òkúta-ọlọ kí o sì lọ ìyẹ̀fun;mú ìbòjú ù rẹ kúrò.Ká yẹ̀rì rẹ sókè, kí o hó ẹṣẹ̀ rẹ sílẹ̀,kí o sì la inú odò lọ.

3. Ìhòòhò rẹ ni a ó fihàn sítaàti ìtìjú rẹ ni a ó sí sílẹ̀.Èmi yóò sì gba ẹ̀ṣan;Èmi kì yóò sì dá ẹnìkan sí.”

4. Olùràpadà wa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀òun ni Ẹni-Mímọ́ Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 47