Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 45:2-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Èmi yóò lọ ṣíwájú rẹèmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹṣẹÈmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹèmi ó sì gé ọ̀pá irin.

3. Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn,ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó farasin,Tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé Èmi ni Olúwa,Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.

4. Nítorí Jákọ́bù ìránṣẹ́ miàti Ísírẹ́lì ẹni tí mo yànMo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ,mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lóríbí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.

5. Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmìíràn;yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan,Èmi yóò fún ọ ní okun,bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,

6. tí o fi jẹ́ pé láti ìlà oòrùntítí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi.

7. Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùnmo mú àlàáfíà wá, mo sì dá àjálù;Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.

Ka pipe ipin Àìsáyà 45