Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 43:25-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọnàìṣedédé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi,tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.

26. Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi,jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀;ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́ṣẹ̀ lọ́rùn.

27. Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀;àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

28. Nítorí náà, èmi yóò dójú ti àwọn ẹni àyẹ́síinú tẹ́ḿpìlìi yín,bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò mú ìparun bá Jákọ́bùàti ìtìjú bá Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 43