25. “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọnàìṣedédé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi,tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
26. Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi,jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀;ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́ṣẹ̀ lọ́rùn.
27. Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀;àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
28. Nítorí náà, èmi yóò dójú ti àwọn ẹni àyẹ́síinú tẹ́ḿpìlìi yín,bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò mú ìparun bá Jákọ́bùàti ìtìjú bá Ísírẹ́lì.