Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 40:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ohùn ẹnìkan tí ń pè:“Nínú ihà ẹ pèṣèọ̀nà sílẹ̀ fún Olúwa:ṣe é kí ó tọ́ ní ihàòpópónà fún Ọlọ́run wa.

4. Gbogbo àfonífojì ni a ó gbé ṣókè,gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀;wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àtiọ̀nà pálapàla ni a yóò sọ di títẹ́jú pẹrẹṣẹ,

5. Ògo Olúwa yóò sì di mímọ̀gbogbo ọmọnìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rii.Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”

6. Ohùn kan wí pé, “Kígbe ṣókè.”Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?”“Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko,àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná inú un pápá.

7. Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀,nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n.Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.

8. Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀,ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”

9. Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Ṣíhónì,lọ sí orí òkè gíga.Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jérúsálẹ́mù,gbé ohùn rẹ ṣókè pẹ̀lú ariwo,gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù;sọ fún àwọn ìlúu Júdà,“Ọlọ́run rẹ nìyìí!”

Ka pipe ipin Àìsáyà 40