Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 40:26-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Gbé ojú rẹ ṣókè kí o sì wo àwọn ọ̀run:Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí?Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kantí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan.Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀,ọ̀kanṣoṣo nínú wọn kò sọnù.

27. Èéṣe tí o fi sọ, Ìwọ Jákọ́bùàti tí o ṣàròyé, Ìwọ Ísírẹ́lì;“Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa;ìṣe mi ni a kò kọbi ara síláti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?

28. Ìwọ kò tí ì mọ̀?Ìwọ kò tí ì gbọ́? Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé,Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀-ayé.Òun kì yóò ṣàárẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì,àti ìmọ̀ rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdiwọ̀n rẹ̀.

29. Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀ó sì fi kún agbára àwọn aláàárẹ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 40