Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 36:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Níbo ni àwọn òrìṣà Hámátì àti Ápádì ha wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Ṣépáfírámù ha wà? Ǹjẹ́ wọn ti já Ṣamáríà gbà kúrò lọ́wọ́ mi bí?

20. Èwo nínú àwọn òrìṣà orílẹ̀ èdè wọ̀nyí ló ha ti dáàbò bo ilẹ̀ẹ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa ṣe wá le gba Jérúsálẹ́mù kúrò lọ́wọ́ mi?”

21. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà dákẹ́ rọ́rọ́ wọn kò sì mú èsì kankan wá, nítorí ọba ti pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”

22. Lẹ́yìn náà ni Eliákímù ọmọ Híkílíà alákóṣo ààfin, Ṣébínà akọ̀wé àti Jóà ọmọ Áṣáfù akọ̀wé àkọsílẹ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Heṣekáyà pẹ̀lú aṣọ wọn ní fífàya, wọ́n sì sọ ohun tí ọ̀gágun ti wí.

Ka pipe ipin Àìsáyà 36