Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 36:14-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ohun tí ọba wí nìyìí: Ẹ má ṣe jẹ́ kí Heṣekáyà tàn yín jẹ. Òun kò le è gbà yín sílẹ̀!

15. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Heṣekáyà rọ̀ yín láti gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nígbà tí ó sọ pé, ‘Olúwa yóò kúkú gbà wá; a kì yóò fi ìlú lé ọba Ásíríà lọ́wọ́.’

16. “Ẹ má ṣe tẹ́tí sí Heṣekáyà. Ohun tí ọba Áṣíríà wí nìyìí: Ẹ ṣètò àlàáfíà pẹ̀lúù mi kí ẹ sì jáde tọ̀ mí wá. Lẹ́yìn náà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò sì jẹ nínú àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mumi nínú kàǹga rẹ̀,

17. títí tí èmi yóò fi mú un yín lọ sí ilẹ̀ kan tí ó dàbí i ti yín, ilẹ̀ tí ó ní irúgbìn oníhóró àti wáìnì tuntun, ilẹ̀ tí ó ní àkàrà àti ọgbà àjàrà.

18. “Ẹ má ṣe jẹ́ kí Heṣekáyà sì yín lọ́nà nígbà tí ó sọ wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá.’ Ǹjẹ́ ọlọ́run orílẹ̀ èdè kan ha ti gbà á kúrò lọ́wọ́ ọba Áṣíríà bí?

Ka pipe ipin Àìsáyà 36