Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 30:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ègbé ni fún orílẹ̀-èdè alágídí náà,”ni Olúwa wí,“Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi,tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi,tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;

2. tí wọ́n lọ sí Éjíbítìláì ṣe fún mi,tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Fáráò fún ààbò,sí òjìji, Éjíbítì fún ibi ìsádi.

3. Ṣùgbọ́n ààbò Fáráò yóò já sí ìtìjú fún un yín,òjìji Éjíbítì yóò mú àbùkù báa yín.

4. Bí wọ́n tilẹ̀ ní àwọn òṣìṣẹ́ ní Sóánìtí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hánísì,

5. gbogbo wọn ni a ó dójútì,nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn,tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá,bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 30