Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 26:7-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́júÌwọ adúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nààwọn olódodo kúnná.

8. Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹàwa dúró dè ọ́;orúkọọ rẹ àti òkìkíì rẹàwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.

9. Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru;ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ.Nígbà tí ìdájọ́ọ̀ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayéàwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.

10. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkàwọn kò kọ́ láti ṣòdodo;kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́ntẹ̀ṣíwájú láti máa ṣe ibiwọn kò sì ka ọlá ńlá Olúwa sí.

11. Olúwa, ti gbé ọwọ́ọ rẹ̀ sókèṣùgbọ́n àwọn kò rí i.Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹkí ojú kí ó tì wọ́n;jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọnọ̀ta rẹ jó wọn run.

12. Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa;ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ nió ṣe é fún wa.

13. Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìírànlẹ́yìn rẹ ti jọba lé wa lórí,ṣùgbọ́n orúkọọ̀ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.

14. Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láàyè mọ́;gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́.Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán,Ìwọ pa gbogbo ìrántíi wọn rẹ́ pátapáta.

15. Ìwọ ti mú orílẹ̀ èdè gbòòrò, Olúwa;ìwọ ti mú orílẹ̀ èdè bí sí i.Ìwọ ti gba ògo fún araàrẹ;ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ ṣẹ́yìn.

16. Olúwa, Wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njúu wọn;nígbà tí o jẹwọ́n ní ìyà,wọ́n tilẹ̀ fẹ́ ẹ̀ má le gbàdúrà kẹ́lẹ́ kẹ́lẹ́.

Ka pipe ipin Àìsáyà 26