Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 26:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa;ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ nió ṣe é fún wa.

13. Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìírànlẹ́yìn rẹ ti jọba lé wa lórí,ṣùgbọ́n orúkọọ̀ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.

14. Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láàyè mọ́;gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́.Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán,Ìwọ pa gbogbo ìrántíi wọn rẹ́ pátapáta.

15. Ìwọ ti mú orílẹ̀ èdè gbòòrò, Olúwa;ìwọ ti mú orílẹ̀ èdè bí sí i.Ìwọ ti gba ògo fún araàrẹ;ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ ṣẹ́yìn.

16. Olúwa, Wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njúu wọn;nígbà tí o jẹwọ́n ní ìyà,wọ́n tilẹ̀ fẹ́ ẹ̀ má le gbàdúrà kẹ́lẹ́ kẹ́lẹ́.

17. Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ bímọtí í rúnra tí ó sì ń sunkún nínú ìrora rẹ̀,bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájúu rẹ Olúwa.

18. Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìroraṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ.Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé;àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.

Ka pipe ipin Àìsáyà 26