Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 26:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Júdà:Àwa ní ìlú alágbára kan,Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣeògiri àti ààbò rẹ̀.

2. Ṣí àwọn ìlẹ̀kùnkí àwọn olódodo orílẹ̀ èdè kí ó lè wọlé,orílẹ̀ èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.

3. Ìwọ yóò paámọ́ ní àlàáfíà pípéọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4. Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé,nítorí Olúwa, Olúwa ni àpátaayérayé náà.

5. Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀;ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹṣẹó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.

6. Ẹṣẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ẹṣẹ̀ aninilára n nì,ipaṣẹ̀ àwọn òtòsì.

7. Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́júÌwọ adúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nààwọn olódodo kúnná.

Ka pipe ipin Àìsáyà 26