Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 23:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò Náì,Ìwọ ọmọbìnrin Táṣíṣì,nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.

11. Olúwa ti na ọwọ́ọ rẹ̀ jáde sí orí òkunó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Fonísíàpé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.

12. Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́”ìwọ wúndíá ti Ṣídónì, tí a ti tẹ̀rẹ́ báyìí!“Gbéra, rékọjá lọ sí Ṣáípúrọ́sì,níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”

13. Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Bábílónì,àwọn ènìyàn tíkò jámọ́ nǹkankan bàyìíÀwọn Ásíríà ti sọ ọ́ diibùgbé àwọn ohun abẹ̀mí ihà;wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gun wọn ṣókè,wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòòhòwọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.

14. Pohùnréré, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Táṣíṣì;wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!

15. Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tírè fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tírè gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:

Ka pipe ipin Àìsáyà 23