Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 21:9-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀wá yìínínú kẹ̀kẹ́ ogunàti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin.Ó sì mú ìdáhùn padà wá:‘Bábílónì ti ṣubú, ó ti ṣubú!Gbogbo àwọn ère òrìṣàa rẹ̀ló fọ́nká lórí ilẹ̀!’”

10. Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gúnmọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà,mo sọ ohun tí mo ti gbọ́láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun,láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

11. Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Dúmáhì:Ẹnìkan ké sí mi láti Séírì wá“Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”

12. Alóre náà dáhùn wí pé,“Òwúrọ̀ súnmọ́tòsí, àti òru náà pẹ̀lú.Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrèkí o sì tún dẹ̀yìn padà wá.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 21