12. Alóre náà dáhùn wí pé,“Òwúrọ̀ súnmọ́tòsí, àti òru náà pẹ̀lú.Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrèkí o sì tún dẹ̀yìn padà wá.”
13. Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Arábíyà:Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dídánítì,tí ó pàgọ́ sínú igbó Arábíyà,
14. gbé omi wá fún àwọn tí òùngbẹ ń gbẹ;ẹ̀yin tí ó ń gbé Tẹ́mà,gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
15. Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà,kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ,kúrò lọ́wọ́ ọrun tí ó lòàti kúrò nínú ìgbóná ogun.
16. Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrin ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ayẹkẹ Kédárì yóò wá sí òpin.