Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 7:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. “Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dáfídì pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Ísírẹ́lì.

9. Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sáà gé gbogbo àwọn ọ̀ta rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.

10. Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Ísírẹ́lì, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó ti wọn, wọn kì yóò sì ṣípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójú mọ́, bí ìgbà àtijọ́.

11. Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Ísírẹ́lì, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ.“ ‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ:

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 7