Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 7:27-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. “Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogún, Ọlọ́run Ísírẹ́lì ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.

28. Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ jèẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.

29. Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ: nítorí ìwọ, Olúwa Ọlọ́run, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípaṣẹ̀ ìbùkún rẹ.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 7