Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 7:18-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Dáfídì ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé:“Olúwa Ọlọ́run, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?

19. Nǹkan kékeré ni èyí sáà jásí lójú rẹ, Olúwa Ọlọ́run; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí há ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Ọlọ́run?

20. “Àti kín ní ó tún kù tí Dáfídì ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Ọlọ́run mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.

21. Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.

22. “Ìwọ sì tóbi, Olúwa Ọlọ́run: kò sì sí ẹni tí ó dà bí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.

23. Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dà bí àwọn ènìyàn rẹ, àní Ísírẹ́lì, àwọn tí Ọlọ́run lọ ràpadà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Éjíbítì wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.

24. Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Ísírẹ́lì kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.

25. “Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.

26. Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Ísírẹ́lì!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dáfídì ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 7