Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 7:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíká kiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.

2. Ọba sì wí fún Nátánì wòlíì pé, “Sá wò ó: èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kédárì kọ́, ṣùgbọ́n àpótí-ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”

3. Nátanì sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”

4. Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Nátánì wá pé:

5. “Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dáfídì, pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.

6. Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gòkè ti ilẹ̀ Éjíbítì wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.

7. Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Ísírẹ́lì, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Ísírẹ́lì, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kédárì kọ́ ilé fún mi.” ’

8. “Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dáfídì pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Ísírẹ́lì.

9. Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sáà gé gbogbo àwọn ọ̀ta rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 7