1. Nígbà tí ọmọ Ṣọ́ọ̀lù sì gbọ́ pé, Ábínérì kú ní Hébírónì, ọwọ́ rẹ̀ sì rọ, gbogbo Ísírẹ́lì sì rẹ̀wẹ̀sì.
2. Ọmọ Ṣọ́ọ̀lù sì ní ọkùnrin méjì tí í ṣe olórí ẹgbẹ́ ogun: a ń pe orúkọ ọ̀kan ní Báánà, àti orúkọ ìkẹjì ní Rákábù, àwọn ọmọ Rímímónì ará Béérótì ti àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì (nítorí pé a sì ka Béérótì pẹ̀lú Bẹ́ńjámínì).