Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 23:22-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Nǹkan wọ̀nyí ní Banáyà ọmọ Jéhóíádà ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà.

23. Nínú àwọn ọgbọ̀n náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dáfídì sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.

24. Ásáhélì arákùnrin Jóábù sì Jásí ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n náà;Élíhánánì ọmọ Dódò ti Bẹ́tílẹ́hẹ́mù;

25. Ṣámà ará Háródì,Élíkà ará Háródì.

26. Hélésì ará Pálitì,Irá ọmọ Íkéṣì ará Tékóà;

27. Ábíésérì ará Ánétótì,Móbúnnáì Húṣátítì;

28. Sálímónì ará Áhóhì,Máháráì ará Nétófà;

29. Hélébù ọmọ Báánà, árá Nétófà,Íttaì ọmọ Ríbáì to Gíbéà ti àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì;

30. Bénáyà ará Pírátónì,Hídáyì tí àfonífojì.

31. Ábíálíbónì ará Áríbà,Ásámífétì Báríhúmítì;

32. Élíáhíbà ará Sáálíbónì,Jáṣénì Gísónítì,Jónátanì;

33. Ṣámà ará Hárárì,Áhíámù ọmọ Ṣárárì ará Hárárì;

34. Élífélétì ọmọ Áhásibáyì, ọmọ ará Máákíhà,Élíámù ọmọ Áhítófélì ará Gílónì;

35. Hésiráì ará Kérímélì,Páárì ará Áríbà;

36. Ígálì ọmọ Nátanì ti Sóbà,Bánì ará Gádì;

37. Sélékì ará Ámónì,Náhárì ará Béérótì, ẹni tí ń ru ìhámọ́ra Jóábù ọmọ Sérúíà;

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 23