22. Nǹkan wọ̀nyí ní Banáyà ọmọ Jéhóíádà ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà.
23. Nínú àwọn ọgbọ̀n náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dáfídì sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.
24. Ásáhélì arákùnrin Jóábù sì Jásí ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n náà;Élíhánánì ọmọ Dódò ti Bẹ́tílẹ́hẹ́mù;
25. Ṣámà ará Háródì,Élíkà ará Háródì.
26. Hélésì ará Pálitì,Irá ọmọ Íkéṣì ará Tékóà;
27. Ábíésérì ará Ánétótì,Móbúnnáì Húṣátítì;
28. Sálímónì ará Áhóhì,Máháráì ará Nétófà;
29. Hélébù ọmọ Báánà, árá Nétófà,Íttaì ọmọ Ríbáì to Gíbéà ti àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì;
30. Bénáyà ará Pírátónì,Hídáyì tí àfonífojì.
31. Ábíálíbónì ará Áríbà,Ásámífétì Báríhúmítì;
32. Élíáhíbà ará Sáálíbónì,Jáṣénì Gísónítì,Jónátanì;
33. Ṣámà ará Hárárì,Áhíámù ọmọ Ṣárárì ará Hárárì;
34. Élífélétì ọmọ Áhásibáyì, ọmọ ará Máákíhà,Élíámù ọmọ Áhítófélì ará Gílónì;
35. Hésiráì ará Kérímélì,Páárì ará Áríbà;