Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 22:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Dáfídì sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀ta rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Sọ́ọ̀lù.

2. Ó sì wí pé,“Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;

3. Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò,àti ìwọ ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi,àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi;ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.

4. Èmi képe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn,ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

5. “Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri;tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.

6. Ọ̀já isà-òkú yí mi káàkiri;ìkẹ́kùn ikú dojú kọ mí.

7. Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa,èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi.Ó sí gbóhùn mi láti tẹ́ḿpìlì rẹ̀igbe mí wọ etí rẹ̀.

8. “Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì;ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì,ó sì mì, nítorí tí ó bínú.

9. Èéfín sì jáde láti ihò-imú rẹ̀ wá;iná láti ẹnu rẹ̀ wá,ó sì ń jónirun, ẹ̀yín sì ń ràn nípasẹ rẹ̀.

10. Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀;òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.

11. Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò:a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 22