Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 21:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dáfídì ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dáfídì sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, Nítorí ti Ṣọ́ọ̀lù ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gíbíónì.

2. Ọba sì pe àwọn ará Gíbíónì, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gíbíónì kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Ámórì; àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ti búra fún wọn: Ṣọ́ọ̀lù sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì àti Júdà.

3. Dáfídì sì bi àwọn ará Gíbíónì léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kìn ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 21