Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 2:29-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Ábínérì àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì fi gbogbo òru náà rìn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì kọjá Jọ́dánì, wọ́n sì rìn ní gbogbo Bítírónì, wọ́n sì wá sí Mahanáímù.

30. Jóábù sì dẹ́kún àti máa tọ Ábínérì lẹ́yìn: ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ, ènìyàn mọ́kándínlógún ni ó kú pẹ̀lú Áṣáhélì nínú àwọn ìránṣẹ Dáfídì.

31. Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ Dáfídì sì pá nínú àwọn ènìyàn Bẹ́ńjámínì: nínú àwọn ọmọkùnrin Ábínérì; òjìdínní-rinwó ènìyàn.

32. Wọ́n si gbé Ásáhélì wọ́n sì sinín sínú ibojì baba rẹ̀ tí ó wà ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù. Jóábù àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ fi gbogbo òru náà rìn, ilẹ̀ sì mọ́ wọn sí Hébírónì.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 2