1. Lẹ́yìn àkókò yìí, Dáfídì wádìí lọ́wọ́ Olúwa. Ó sì béèrè pé, “Ṣé èmi lè gòkè lọ sí ọ̀kan lára àwọn ìlú Júdà?” Olúwa sì wí pé, “Gòkè lọ.”Dáfídì sì béèrè pé, “Ní ibo ni kí èmi kí ó lọ?” Olúwa sì dáa lóhùn pé, “Sí Hébúrónì.”
2. Nígbà náà ni Dáfídì gòkè lọ ṣíbẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ méjì Áhínóámù ará Jésérẹ́lì, àti Ábígáílì obìnrin opó Nábálì ti Kámẹ́lì.