Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 19:20-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé èmi ti ṣẹ̀; sì wòó, mo wá lónìí yìí, ẹni àkọ́kọ́ ní gbogbo ìdílé Jósẹ́fù tí yóò sọ̀kalẹ̀ wá pàdé Olúwa mi ọba.”

21. Ṣùgbọ́n Ábíṣáì ọmọ Serúíà dáhùn ó sì wí pé, “Kò há tọ́ kí a pa Síméì nítorí èyí? Nítorí pé òun ti bú ẹni àmì òróró Olúwa.”

22. Dáfídì sì wí pé, “Kí ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Serúíà tí ẹ dàbí ọ̀ta fún mi lónìí? A há lè pa ènìyàn kan lónìí ní Ísírẹ́lì? Tàbí èmi kò ha mọ̀ pé lónìí èmi ni ọba Ísírẹ́lì.”

23. Ọba sì wí fún Ṣíméhì pé, “Ìwọ kì yóò kú!” Ọba sì búra fún un.

24. Méfíbóṣetì ọmọ Ṣọ́ọ̀lù sì sọ̀kalẹ̀ láti wá pàdé ọba, kò wẹ ẹṣẹ̀ rẹ̀, kò sí tọ́ irungbọ̀n rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fọ aṣọ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ọba ti jáde títí ó fi di ọjọ́ tí ó fi padà ní àlàáfíà.

25. Nígbà tí òun sì wá sí Jérúsálẹ́mù láti pàdé ọba, ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ kò fi bá mi lọ, Méfíbóṣétì?”

26. Òun sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, Ọba, ìránṣẹ́ mi ni ó tàn mí, nítorí ìránṣẹ́ rẹ wí fún un pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi èmi ó gùn ún, èmi ó sì tọ ọba lọ.’ Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ yarọ.

27. Ó sì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí ìránṣẹ́ rẹ, fún Olúwa mi ọba, ṣùgbọ́n bí áńgẹ́lì Ọlọ́run ni Olúwa mi ọba rí: nítorí náà ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ.

28. Nítorí pé gbogbo ilé baba mi bí òkú ènìyàn ni wọ́n sáà rí níwájú Olúwa mi ọba: ìwọ sì fi ipò fún ìránṣẹ́ rẹ láàrin àwọn tí ó ń jẹ́un ní ibi oúnjẹ́. Nítorí náà àre kín ni èmi ní tí èmi yóò fi máa ké pe ọba síbẹ̀.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 19