Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 18:25-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Álóre náà sì kígbe, ó sì wí fún ọba.Ọba sì wí pé, “Bí ó bá ṣe òun nìkan ni, ìhìn rere ń bẹ lẹ́nu rẹ̀.” Òun sì ń súnmọ́ tòsí.

26. Álóre náà sì rí ọkùnrin mìíràn tí ń sáré: Alóre sì kọ sí ẹni tí ń ṣọ́ bodè, ó sì wí pe, “Wò ó, ọkùnrin kan ń sáré òun nìkan.”Ọba sì wí pé, “Èyí náà pẹ̀lú ń mú ìhìn rere wá.”

27. Álóre náà sì wí pé, “Èmi wo ìsáre ẹni tí ó wà níwájú ó dàbí ìsáré Áhímásì ọmọ Sádókù.”Ọba sì wí pé, “Ènìyàn re ni, ó sì ń mú ìhìn rere wá!”

28. Áhímásì sì dé, ó sì wí fún ọba pé, “Àlàáfíà!” Ó sì wólẹ̀ fún ọba, ó dojúbolẹ̀ ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó fi àwọn ọkùnrin tí ó gbé ọwọ́ wọn sókè sí Olúwa mi ọba lé ọ lọ́wọ́.”

29. Ọba sì béèrè pé, “Àlàáfíà ha wà fún Ábúsálómù, ọmọdékùnrin náà bí?”Áhímásì sì dáhùn pé, “Nígbà tí Jóábù rán ìránṣẹ́ ọba, àti èmi ìránṣẹ́ rẹ̀, mo rí ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ìdí rẹ̀.”

30. Ọba sì wí fún un pé, “Yípadà kí o sì dúró nìhìn-ín.” Òun sì yípadà, ó sì dúró jẹ́ẹ́.

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 18