Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 9:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti-Gílíádì.

5. Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí.“Fún èwo nínú wa?” Jéhù béèrè.“Fún ọ, Alákóso,” Ó dáhùn.

6. Jéhù dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jéhù; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Ísírẹ́lì.

7. Kí ìwọ kí ó pa ilé Áhábù ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jésébélì.

8. Gbogbo ilé Áhábù yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Áhábù gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Ísírẹ́lì, ẹrú tàbí òmìnira.

9. Èmi yóò ṣe ilé Áhábù gẹ́gẹ́ bí ilé Jéróbóhámù ọmọ Nábátì àti ilé Bááṣà ọmọ Áhíjà.

Ka pipe ipin 2 Ọba 9