Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 9:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Wòlíì Èlíṣà fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti-Gílíádì.

2. Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jéhù ọmọ Jéhóṣáfátì, ọmọ Mímísì kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.

3. Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi fi àmì òróró yàn Ọ́ ní ọba lórí Ísírẹ́lì.’ Nígbà náà, sí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré; Má ṣe jáfara!”

4. Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti-Gílíádì.

Ka pipe ipin 2 Ọba 9