Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 3:11-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ṣùgbọ́n Jèhóṣáfátì sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Ísírẹ́lì dáhùn pé, “Èlíṣà ọmọ Ṣáfátì wà níbí. Ó máa ṣábà bu omi sí ọwọ́ Èlíjàh.”

12. Jèhóṣáfátì wí pé, “ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Ísírẹ́lì àti Jèhóṣáfátì àti ọba Édómù sọ̀ kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.

13. Èlíṣà wí fún ọba Ísírẹ́lì pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì bàbá rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.”“Rárá,” ọba Ísírẹ́lì dá a lóhùn, “nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Móábù lọ́wọ́.”

14. Èlíṣà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jèhósáfátì ọba Júdà, Èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.

15. Ṣùgbọ́n Nísinsìn yìí mú wá fún mi ohun èlò orin olókun.”Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Èlíṣà.

Ka pipe ipin 2 Ọba 3