Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 25:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí ó di ọdún kẹsàn án ìjọba Ṣédékíàyà. Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹwàá, Nebukadinésárì ọba Bábílónì yan lọ sí Jérúsálẹ́mù pẹ̀lú gbogbo àwọn ogun rẹ̀. Ó sì pàgọ́ sí ìta ìlú ó sì mu àwọn isẹ ìdọ̀tì fi yí gbogbo rẹ̀ ká.

2. Ìlú náà sì wà ní ìhámọ́ lábẹ́ ìdọ̀tí títí di ọdún kọkànlá ti ọba Ṣédékíáyà.

3. Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kẹrin, iyàn tí mú ní ìlú tí ó jẹ́ wí pé kò sí oúnjẹ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.

4. Nígbà náà odi ìlú náà sì fón ká, gbogbo àwọn ọmọ ogun sá lọ ní òru láti ẹnu ọ̀nà bodè láàrin ògiri méjì ní ẹgbẹ́ ọgbà ọba, lára àwọn ará Bábílónì wọ́n sì yí ìlú náà ká. Wọ́n sá lọ sí ìkọjá Árábù.

5. Ṣùgbọ́n ogun àwọn ará kalídíà sì lépa ọba, wọ́n sì lée bá ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jéríkò. Gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ sì yà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì túká,

6. Wọ́n sì mú un wọ́n sì mú lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Bábílónì ní Ríbílà, níbi tí à ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.

7. Wọ́n sì pa ọmọ Ṣédékáyà níwájú rẹ̀, wọ́n sì yọ ojú rẹ̀ jáde, wọn dèé pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n idẹ wọ́n sì gbe é lọ sí Bábílónì.

Ka pipe ipin 2 Ọba 25