Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 16:2-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ẹni ogún ọdún ni Áhásì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí jọba, ó sì jọba ọdún mẹ́rìndínlógún ní Jérúsálẹ́mù, kò si ṣe èyí tí ó tọ́ lójú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Dáfídì baba rẹ̀.

3. Ṣùgbọ́n ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Ísíráẹ́lì, nítòótọ́, ó sì mú kí ọmọ rẹ̀ ó kọjá láàrin iná, gẹ́gẹ́ bi iṣẹ́ ìrírà àwọn aláìkọlà, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Ísíráẹ́lì.

4. Ó sì rúbọ, ó sì ṣun tùràrí ní àwọn ibi gíga, àti lórí àwọn òkè kéékèèkéé àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.

5. Nígbà náà ni Résínì ọba Ṣíríà àti Pẹ́kà ọmọ Rèmálíà ọba Ísíráẹ́lì gòkè wá sí Jérúsálẹ́mù láti jagun: wọ́n dó ti Áhásì, ṣùgbọ́n wọn kò lè borí rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Ọba 16