2 Ọba 13:25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)
Nígbà náà, Jéhóásì ọmọ Jéhóáhásì gbà padà kúrò lọ́wọ́ Bẹni-Hádádì ọmọ Hásáélì àwọn ìlú tí ó ti gbà nínú ogun látọ̀dọ̀ baba rẹ̀ Jéhóáhásì. Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta, Jéhóásì ṣẹ́gun rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó gba ìlú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì padà.