Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 7:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ní ọjọ́ kẹ́jọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyà símímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àṣe náà fún ọjọ́ méje sí i.

10. Ní ọjọ́ kẹtàlélógún (23rd day) tí oṣù kéje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dáfídì àti Sólómónì, àti fún àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.

11. Nígbà tí Sólómónì ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkálárarẹ̀,

12. Olúwa sì farahàn ní òru ó sì wí pé:“Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibííyí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.

13. “Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma báà sí òjò, tàbí láti pàsẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-àrùn sí àárin àwọn ènìyàn mi,

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 7