Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 6:36-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. “Nígbà tí wọ́n bá sì dẹ́sẹ̀ sí ọ-nítorí kò sí ènìyàn kan tí kò dẹ́sẹ̀-bí o bá sì bínú sí wọn tí o bá sì fi wọ́n fún àwọn ọ̀tá, tí wọ́n kó wọn ní ìgbèkùn sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré tàbí nítòsí,

37. Ṣùgbọ́n, nígbà tí, wọ́n bá sì yí ọkàn wọn padà ní ilẹ̀ tí wọ́n ti mú wọn ní ìgbèkùn, tí wọ́n sì ronú pìwàdà tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn, wọn ó sì wí pé, Àwa ti dẹ́sẹ̀, àwa sì ti ṣe ohun tí kò dára, a sì ti ṣe búburú.

38. Tí wọn bá sì yípadà sí ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn àti ẹ̀mí ní ilẹ̀ ìgbèkùn wọn níbi tí wọ́n ti mú wọn, tí wọ́n sì gbàdúrà wọn, lórí ìlú tí ìwọ ti yàn àti lórí ilé Olúwa tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ;

39. Nígbà náà, láti ọ̀run, ibi ibùgbé rẹ, gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn jìn wọn, tí ó ti dẹ́sẹ̀ sí ọ.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 6