Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 4:13-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ọgọ́rùn ún mẹ́rin Pomígíránátì fún iṣẹ́ ẹ̀wọ̀n méjì naà, ẹṣẹ̀ méjì Pomigiranati ni fún iṣẹ́ ẹ̀wọ̀n kan, láti bo ọpọ́n rìbìtì méjì náà tí ó wà lóri àwọn òpó náà;

14. Ó sì ṣe àgbéró ó sì ṣe agbada sí orí wọn;

15. Agbada ńlá kan àti màlúù méjìlá lábẹ́ rẹ̀;

16. Àwọn ìkòkò àti ọ̀kọ̀ àti àmúga ẹran àti gbogbo ohun èlò tí ó fara pẹ́ẹ.Gbogbo ohun èlò ti Húrámí-bì fi idẹ dídán ṣe fún Sólómónì ọba, fún ilé Olúwa jẹ́ idẹ dídán.

17. Ọba dà wọ́n ní ilẹ̀ amọ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jọ́dánì ní àárin méjì Súkótì àti Ṣárétánì.

18. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí Sólómónì ṣe ní iye lórí púpọ̀ tí a kò le mọ ìwọ̀n iye idẹ tí ó wọ̀n.

19. Sólómónì pẹ̀lú ṣe gbogbo ohun èlò tí ó wà ní ilé Ọlọ́run:pẹpẹ wúràtábìlì èyí tí àkàrà ìfihàn wà lórí rẹ̀;

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 4