21. Ìlẹ̀ náà sì gbádùn ìsinmi rẹ̀, ní gbogbo ìgbà ìdahoro, òun sì ń sinmi títí ó fi di àádọ́rin ọdún (70) fi pé ní ìmúsẹ ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ láti ẹnu Jeremíà.
22. Ní ọdún kín-ín-ní Kírúsì ọba Pásíà, kí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a tẹnu Jeremáyà sọ báà le ṣẹ pé, Olúwa run ẹ̀mí Kírúsì ọba Pásíà láti ṣe ìkéde ní gbogbo ìjọba rẹ̀, ó sì kọọ́ sínú ìwé pẹ̀lú.
23. “Èyí ni ohun tí Kérúsì ọba Pásíà sọ wí pé:“ ‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mí ní gbogbo ìjọba ayé yìí, ó sì ti yàn mí láti kọ́ ilé Olúwa fún òun ní Jérúsálẹ́mù ti Júdà. Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàárin yín le gòkè lọ pẹ̀lú rẹ̀; kí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ kí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.’ ”