Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 24:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jóásì jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ogójì ọdún. Orúkọ ìya rẹ̀ ni Ṣíbíà ti Béríṣébà.

2. Jóásì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jéhóiádà àlùfáà.

3. Jéhóiádà yan ìyàwó méjì fún-un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.

4. Ní àkókò kan, Jóásì pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.

5. Ó pe Àwọn Àlùfáà àti àwọn ará Léfì jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Júdà, kí ẹ sì gba owó ìtọ̀sì lati ọwọ́ gbogbo Ísírẹ́lì láti fi tún ilé Ọlọ́run ṣe, ṣé nísinsìn yìí” Ṣùgbọ́n àwọn ará Léfì kò ṣe é lẹ́ẹ́kan naà.

6. Nítorí náà ọba paálásẹ fún Jéhóiádà olorí àlùfáà ó sì wí fún-un pé, “Kí ni ó dé tí o kò, bèèrè lọ́wọ́ àwọn ará Léfì láti mú wá láti Júdà àti Jérúsálẹ́mù, owó orí tí Mósè ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Ísírẹ́lì fún àgọ́ ìjẹ́rìí?”

7. Nísinsinyí, àwọn ọmọkùnrin, obìnrin búburú ni Ataláyà ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Báálì.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 24