Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 21:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà Jéhóṣáfátì sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dáfídì. Jéhórámù ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

2. Àwọn ará kùnrin Jéhóramù ọmọ Jéhóṣáfatì jẹ́ Áṣáríyà, Jèhíeli, Ṣekárià. Ásáríyàhù, Míkáélí àti Ṣefátíá. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jéhóṣafátì ọba Ìsírẹlì.

3. Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bun púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Júdà, Ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jéhóramù nítori òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.

4. Nígbà tí Jéhórámù fi ara rẹ̀ lélẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó pa gbogbo àwọn arákùrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìrin ọba Ìsirẹ́lì.

5. Jéhórámù jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún méjọ.

6. Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìdílé Áhábù ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìrin Áhábù. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.

7. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dáfídì kì í ṣe ífẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dáfídì run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 21