Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 6:17-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Fílístínì fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Ásídódù, ọ̀kan ti Gásà, ọ̀kan ti Ásíkélónì, ọ̀kan ti Gátì, ọ̀kan ti Ékírónì.

18. Góòlù eku-ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Fílístínì márààrún ti wá, ìlú olodi pẹ̀lú ìlétò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Jóṣúà ará Bẹti-Sémésì.

19. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọ lu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Bẹti-Sémésì, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.

20. Àwọn ọkùnrin ará Bẹti-Sémésì béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”

21. Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati Jéárímì wí pé, “àwọn Fílístínì ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 6