Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:8-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Éjíbítì pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-àrùn ní ihà.

9. Ẹ jẹ́ alágbára Fílístínì, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Hébérù, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín: Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”

10. Nígbà náà àwọn Fílístínì jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Ísírẹ́lì olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn; Àwọn ará Ísírẹ́lì tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàámẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ ogun orí ilẹ̀ (30,000).

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4