Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 4:12-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Lọ́jọ́ kan náà tí ará Bẹ́ńjámínì kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣílò, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.

13. Nígbà tí ó sì dé, Élì sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sunkún

14. Élì gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtúmọ̀ ariwo yìí?”Ọkùnrin náà sì sáré tọ Élì wá

15. ẹni tí ó jẹ́ ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ kò sì ríran mọ́.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 4