Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 31:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn Fílístínì sì bá Ísírẹ́lì jà: àwọn ọkùnrin Ísírẹlì sì sá níwájú àwọn Fílístínì, àwọn tí ó fi ara pa sì ṣubú ní òkè Gílíbóà.

2. Àwọn Fílístínì sì ń lépa Ṣọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ rẹ̀ kíkan; àwọn Fílístínì sì pa Jónátanì àti Ábínádábù, àti Mélíkísúà, àwọn ọmọ Ṣọ́ọ̀lù.

3. Ìjà náà sì burú fún Ṣọ́ọ̀lù gidigidi, àwọn tafàtafà si ta á ní ọfà, o sì fi ara pa púpọ̀ lọ́wọ́ àwọn tafàtafà.

4. Ṣọ́ọ̀lù sì wí fún ẹni tí o ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí ìwọ sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má ba à wá gún mi, àti kí wọn kí ó má bá à fi mí ṣe ẹlẹ́yà.”Ṣùgbọ́n ẹni tí ó rú ẹ̀rù ìhámọ́ra rẹ̀ kò fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí pé ẹ̀rù bà á gidigidi. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù mú idà, ó sì ṣubú lù ú.

5. Nígbà tí ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ si ríi pé Ṣọ́ọ̀lù kú, òun náà sì fi idà rẹ̀ pá ara rẹ̀, ó sì kú pẹ̀lú rẹ̀.

6. Ṣọ́ọ̀lù sì kú, àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta, àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọkùrin rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.

7. Nígbà ti àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì tí ó wà lápa kejì àfonífojì náà, àti àwọn ẹni tí ó wà lápá kejì Jódánì, rí pé àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sá, àti pé Ṣọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọkùnrin rẹ ti kú, wọ́n sì fí ìlú sílẹ̀, wọ́n sì sá, àwọn Fílístínì sí wá, wọ́n sì jókòó si ìlú wọn.

8. Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn Fílístínì dé láti bọ́ nǹkán tí ń bẹ lára àwọn tí ó kù, wọ́n sì rí pé, Ṣọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́ta ṣubú ni òkè Gílíbóà.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 31