18. Sámúẹ́lì sọ gbogbo rẹ̀ fún un, kò sì fi ohun kankan pamọ́ fún un. Nígbà náà Élì wí pé, “Òun ni Olúwa; jẹ́ kí ó ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.”
19. Olúwa wà pẹ̀lú Sámúẹ́lì bí ó ṣe ń dàgbà, kò sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ kùnà.
20. Gbogbo Ísírẹ́lì láti Dánì títí dé Bíáṣébà mọ̀ pé a ti fa Sámúẹ́lì kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì Olúwa.
21. Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ara hàn-án ní Ṣílò, nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀.