Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 28:21-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Obìnrin náà sì tọ Ṣọ́ọ̀lù wá, ó sì rí i pé ó wà nínú ìbànújẹ́ púpọ̀, ó sì wí fún un pé, “Wò ó, ìránṣẹ́bìnrin rẹ́ ti gbọ́ ohun rẹ̀, èmi sì ti fi ẹ̀mi mi sí ọwọ́ mi, èmi sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ti ìwọ sọ fún mi.

22. Ǹjẹ́, nísinsìnyìí èmi bẹ̀ ọ́, gbọ́ ohùn ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi yóò sì fi oúnjẹ díẹ̀ ṣíwájú rẹ̀; sì jẹun, ìwọ yóò sì lágbára, nígbà tí ìwọ bá ń lọ lọ́nà.”

23. Ṣùgbọ́n ó kọ̀, ó sì wí pé, “Èmi kì yóò jẹun.”Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rọ̀ ọ́. Ó sì dide kúrò ni ilẹ̀, ó sì jókòó lorí àkéte.

24. Obìnrin náà sì ni ẹgbọrọ màlúù kan ti ó sańra ni ilé, ó sì yára, ó pa á, ó sì mú ìyẹ̀fún, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà àìwú.

25. Ó sì mú un wá ṣíwájú Ṣọ́ọ̀lù, àti ṣíwájú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀; wọ́n sì jẹun. Wọ́n sì dìde, wọ́n lọ ní òru náà.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 28